Gbọ Audio Ìròyìn Òmìnira

Ìròhìn tí ó tẹ̀ wá lọ́wọ́ sọ pé olórí kan ní ìlú Japan ti tọrọ àforíjì lọ́wọ́ àwọn tó kọ̀ pé àwọn ò ní gba abẹ́rẹ́-àjẹsára covid, látàrí pé àwọn mọ̀ pé wọ́n fẹ́ fi ṣekúpa’ni ni.

Ó ní, “ẹ̀yin tí ẹ kọ̀ láti gba abẹ́rẹ́ àjẹsára yẹn, ẹ ti jàre mi o, Òótọ́ ni ẹ sọ nígbànáà lọ́hun, mílíọ̀nù mílíọ̀nù àwọn èèyàn wa ló nkú, látàrí gbígba abẹ́rẹ́  àjẹsára. Ẹ foríjì mí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ti kú báyi, tí kò sì yẹ kí wọ́n kú.”

Ṣebí ẹni tí ó sọ òótọ́ nì yẹn; níbẹ̀ ni àwọn míràn á ṣáà rọn’rí mọ pé àwọn onímọ̀-ìjìnlẹ̀ ti sọ pé kí àwọn lọ gbàá, àwọn dẹ̀ nlọ gbàá! Onímọ̀-ìjìnlẹ̀ aṣekúpani ntì ẹ́, ìwọ náà nlọ sí’bi ìpàrun tí ó ntìẹ́ lọ.

Ọmọ Ìbílẹ̀ Yorùbá (Indigenous Yoruba People, I.Y.P) ti Democratic Republic of the Yoruba (D.R.Y), Olódùmarè tí ó nfi ọ̀nà han Màmá wa, Ìyá-Ààfin Modúpẹ́ Onítirí-Abíọ́lá, tí wọ́n dẹ̀ ntẹ̀lée, ni kí a máa tẹ̀lé o, kí á má ṣe kábamọ̀ ohun tí kò yẹ kí á kó sínú rẹ̀.

Ká Ìròyìn Síwájú sí: